Surah Al-Alaq in Yoruba

    العلق

    Surah Al-Alaq in Yoruba

    Read Surah Al-Alaq in Yoruba (العلق) with Arabic text, Yoruba translation, and audio recitation. Chapter 96 of the Holy Quran, 19 verses — free online.

    Quran in Yoruba · all 114 Surahs

    1

    ٱقۡرَأۡ بِٱسۡمِ رَبِّكَ ٱلَّذِي خَلَقَ

    Ké (al-Ƙur’ān) pẹ̀lú orúkọ Olúwa rẹ, Ẹni tí Ó dá ẹ̀dá.

    2

    خَلَقَ ٱلۡإِنسَٰنَ مِنۡ عَلَقٍ

    Ó ṣẹ̀dá ènìyàn láti ara ẹ̀jẹ̀ dídì.

    3

    ٱقۡرَأۡ وَرَبُّكَ ٱلۡأَكۡرَمُ

    Ké e. Olúwa rẹ ni Alápọ̀n-ọ́nlé jùlọ.

    4

    ٱلَّذِي عَلَّمَ بِٱلۡقَلَمِ

    Ẹni tí Ó fi ìmọ̀ nípa gègé ìkọ̀wé mọ ènìyàn.

    5

    عَلَّمَ ٱلۡإِنسَٰنَ مَا لَمۡ يَعۡلَمۡ

    Ó fi ìmọ̀ tí ènìyàn kò mọ̀ mọ̀ ọ́n.

    6

    كَلَّآ إِنَّ ٱلۡإِنسَٰنَ لَيَطۡغَىٰٓ

    Ní ti òdodo, dájúdájú ènìyàn kúkú ń tayọ ẹnu-ààlà

    7

    أَن رَّءَاهُ ٱسۡتَغۡنَىٰٓ

    nítorí pé ó rí ara rẹ̀ ní ọlọ́rọ̀.

    8

    إِنَّ إِلَىٰ رَبِّكَ ٱلرُّجۡعَىٰٓ

    Dájúdájú ọ̀dọ̀ Olúwa rẹ ni àbọ̀ ẹ̀dá.

    9

    أَرَءَيۡتَ ٱلَّذِي يَنۡهَىٰ

    Sọ fún mi nípa ẹni tó ń kọ̀

    10

    عَبۡدًا إِذَا صَلَّىٰٓ

    fún ẹrúsìn kan nígbà tí (ẹrúsìn náà) kírun!

    11

    أَرَءَيۡتَ إِن كَانَ عَلَى ٱلۡهُدَىٰٓ

    Sọ fún mi (nípa ẹ̀san rẹ̀) tí ó bá jẹ́ pé ó wà lórí ìmọ̀nà (’Islām)

    12

    أَوۡ أَمَرَ بِٱلتَّقۡوَىٰٓ

    tàbí pé ó pàṣẹ ìbẹ̀rù (Allāhu)!

    13

    أَرَءَيۡتَ إِن كَذَّبَ وَتَوَلَّىٰٓ

    Sọ fún mi (nípa ìyà rẹ̀) tí ó bá jẹ́ pé ó pe òdodo ní irọ́, tí ó sì kẹ̀yìn sí i?

    14

    أَلَمۡ يَعۡلَم بِأَنَّ ٱللَّهَ يَرَىٰ

    Ṣé kò mọ̀ pé dájúdájú Allāhu ń rí (òun ni?)

    15

    كَلَّا لَئِن لَّمۡ يَنتَهِ لَنَسۡفَعَۢا بِٱلنَّاصِيَةِ

    Rárá (ọ̀rọ̀ kò rí bí ọ̀tá Allāhu ṣe rò ó sí.[1]) Dájúdájú tí kò bá jáwọ́ (níbi dídí Ànábì - kí ìkẹ́ àti ọlà Allāhu máa bá a - lọ́wọ́), dájúdájú A máa fi àásó orí[2] rẹ̀ wọ́ ọ (sínú Iná);

    [1] Ẹni yẹn ni Abu Jahl. [2] àásó orí; irun iwájú orí.

    16

    نَاصِيَةٖ كَٰذِبَةٍ خَاطِئَةٖ

    àásó orí òpùrọ́, ẹlẹ́ṣẹ̀.

    17

    فَلۡيَدۡعُ نَادِيَهُۥ

    Nítorí náà, kí ó pe àwọn olùbájókòó rẹ̀.

    18

    سَنَدۡعُ ٱلزَّبَانِيَةَ

    Àwa máa pe àwọn mọlāika ẹ̀ṣọ́ Iná.

    19

    كَلَّا لَا تُطِعۡهُ وَٱسۡجُدۡۤ وَٱقۡتَرِب۩

    Rárá (ọ̀rọ̀ kò rí bí ó ṣe ń sọ nípa Wa). Má ṣe tẹ̀lé tirẹ̀. Forí kanlẹ̀ (kí o kírun), kí o sì súnmọ́ (Allāhu).

    Al-Alaq

    Play