وَٱلسَّمَآءِ وَٱلطَّارِقِ
(Allāhu) fi sánmọ̀ àti Tọ̄riƙ búra.
الطارق
Read Surah At-Tariq in Yoruba (الطارق) with Arabic text, Yoruba translation, and audio recitation. Chapter 86 of the Holy Quran, 17 verses — free online.
Quran in Yoruba · all 114 Surahs
وَٱلسَّمَآءِ وَٱلطَّارِقِ
(Allāhu) fi sánmọ̀ àti Tọ̄riƙ búra.
وَمَآ أَدۡرَىٰكَ مَا ٱلطَّارِقُ
Kí sì ni ó mú ọ mọ ohun tó ń jẹ́ Tọ̄riƙ?
ٱلنَّجۡمُ ٱلثَّاقِبُ
Ìràwọ̀ tí ìmọ́lẹ̀ rẹ̀ ń tàn ròrò (ní alẹ́ ni).
إِن كُلُّ نَفۡسٖ لَّمَّا عَلَيۡهَا حَافِظٞ
Kò sí ẹ̀mí kan àfi kí ẹ̀ṣọ́ kan wà fún un (nínú àwọn mọlāika).
فَلۡيَنظُرِ ٱلۡإِنسَٰنُ مِمَّ خُلِقَ
Nítorí náà, kí ènìyàn wòye sí ohun tí A fi ṣẹ̀dá rẹ̀.
خُلِقَ مِن مَّآءٖ دَافِقٖ
Wọ́n ṣẹ̀dá rẹ̀ láti inú omi tó ń tú jáde kọ̀ọ́kọ̀ọ́.
يَخۡرُجُ مِنۢ بَيۡنِ ٱلصُّلۡبِ وَٱلتَّرَآئِبِ
Ó ń jáde láti ààrin ìbàdí ọkùnrin àti àwọn ẹfọ́nhà igbá-àyà obìnrin.
إِنَّهُۥ عَلَىٰ رَجۡعِهِۦ لَقَادِرٞ
Dájúdájú Allāhu ni Alágbára lóri ìdápadà rẹ̀
يَوۡمَ تُبۡلَى ٱلسَّرَآئِرُ
ní ọjọ́ tí wọ́n máa ṣe àyẹ̀wò àwọn (iṣẹ́) àṣepamọ́.
فَمَا لَهُۥ مِن قُوَّةٖ وَلَا نَاصِرٖ
Nígbà náà, kò níí sí agbára tàbí alárànṣe kan fún un.
وَٱلسَّمَآءِ ذَاتِ ٱلرَّجۡعِ
Allāhu fi sánmọ̀ tó ń rọ òjò ní ọdọọdún búra.
وَٱلۡأَرۡضِ ذَاتِ ٱلصَّدۡعِ
Ó tún fi ilẹ̀ tó ń sán kànkàn (fún híhùjáde èso) búra.
إِنَّهُۥ لَقَوۡلٞ فَصۡلٞ
Dájúdájú al-Ƙur’ān ni ọ̀rọ̀-ìpínyà (láààrin òdodo àti irọ́).
وَمَا هُوَ بِٱلۡهَزۡلِ
Kì í sì ṣe àwàdà.
إِنَّهُمۡ يَكِيدُونَ كَيۡدٗا
Dájúdájú wọ́n ń déte gan-an.
وَأَكِيدُ كَيۡدٗا
Èmi náà sì ń déte gan-an.[1]
[1] Ẹ wo ìtọsẹ̀-ọ̀rọ̀ fún sūrah al-Baƙọrah; 2:15.
فَمَهِّلِ ٱلۡكَٰفِرِينَ أَمۡهِلۡهُمۡ رُوَيۡدَۢا
Nítorí náà, lọ́ra fún àwọn aláìgbàgbọ́. Lọ́ wọn lára sẹ́ fún ìgbà díẹ̀.
At-Tariq
Play