إِذَا ٱلشَّمۡسُ كُوِّرَتۡ
Nígbà tí wọ́n bá ká òòrùn kóróbójó dànù,
التكوير
Read Surah At-Takwir in Yoruba (التكوير) with Arabic text, Yoruba translation, and audio recitation. Chapter 81 of the Holy Quran, 29 verses — free online.
Quran in Yoruba · all 114 Surahs
إِذَا ٱلشَّمۡسُ كُوِّرَتۡ
Nígbà tí wọ́n bá ká òòrùn kóróbójó dànù,
وَإِذَا ٱلنُّجُومُ ٱنكَدَرَتۡ
àti nígbà tí àwọn ìràwọ̀ bá já bọ́ káàkiri,
وَإِذَا ٱلۡجِبَالُ سُيِّرَتۡ
àti nígbà tí wọ́n bá mú àwọn àpáta rìn (kúrò ní àyè wọn, tí wọ́n kù wọ́n dànù),
وَإِذَا ٱلۡعِشَارُ عُطِّلَتۡ
àti nígbà tí wọ́n bá pa àwọn ràkúnmí aboyún tì,
وَإِذَا ٱلۡوُحُوشُ حُشِرَتۡ
àti nígbà tí wọ́n bá ko àwọn ẹranko jọ,
وَإِذَا ٱلۡبِحَارُ سُجِّرَتۡ
àti nígbà tí wọ́n bá mú àwọn agbami odò gbiná,
وَإِذَا ٱلنُّفُوسُ زُوِّجَتۡ
àti nígbà tí wọ́n bá so àwọn ẹ̀mí pọ̀ mọ́ra wọn, (ẹni rere pẹ̀lú ẹni rere, ẹni ibi pẹ̀lú ẹni ibi)
وَإِذَا ٱلۡمَوۡءُۥدَةُ سُئِلَتۡ
àti nígbà tí ọmọbìnrin tí wọ́n bò mọ́lẹ̀ láàyè bá bèèrè pé
بِأَيِّ ذَنۢبٖ قُتِلَتۡ
ẹ̀ṣẹ̀ wo ni wọ́n pa òun fún,
وَإِذَا ٱلصُّحُفُ نُشِرَتۡ
àti nígbà tí wọ́n bá ṣí àwọn tákàdá (iṣẹ́ ẹ̀dá) sílẹ̀,
وَإِذَا ٱلسَّمَآءُ كُشِطَتۡ
àti nígbà tí wọ́n bá ká sánmọ̀ kúrò lókè,
وَإِذَا ٱلۡجَحِيمُ سُعِّرَتۡ
àti nígbà tí wọ́n bá mú iná Jẹhīm jò fòfò,
وَإِذَا ٱلۡجَنَّةُ أُزۡلِفَتۡ
àti nígbà tí wọ́n bá sún Ọgbà Ìdẹ̀ra mọ́ (àwọn onígbàgbọ́ òdodo),
عَلِمَتۡ نَفۡسٞ مَّآ أَحۡضَرَتۡ
(nígbà náà ni) ẹ̀mí (kọ̀ọ̀kan) yóò mọ ohun tí ó mú wá (nínú iṣẹ́ ire àti iṣẹ́ ibi).
فَلَآ أُقۡسِمُ بِٱلۡخُنَّسِ
Nítorí náà, Èmi (Allāhu) ń fi àwọn ìràwọ̀ tó ń yọ ní alẹ́, tó ń wọ̀ọ̀kùn ní ọ̀sán búra,
ٱلۡجَوَارِ ٱلۡكُنَّسِ
(ìyẹn) àwọn ìràwọ̀ tó ń rìn lọ rìn bọ̀, tó ń wọ̀ọ̀kùn sí ibùwọ̀ wọn.
وَٱلَّيۡلِ إِذَا عَسۡعَسَ
Mo tún fi alẹ́ nígbà tí ó bá lọ búra.[1]
[1] Ìtúmọ̀ mìíràn: Mo tún fi alẹ́ nígbà tí ó bá wọlé búra.
وَٱلصُّبۡحِ إِذَا تَنَفَّسَ
Mo tún fi òwúrọ̀ nígbà tí ó bá mọ́lẹ̀ búra.
إِنَّهُۥ لَقَوۡلُ رَسُولٖ كَرِيمٖ
Dájúdájú (al-Ƙur’ān) ni ọ̀rọ̀ (tí A fi rán Jibrīl) Òjíṣẹ́, alápọ̀n-ọ́nlé,[1]
[1] Wo ìtọsẹ̀-ọ̀rọ̀ sūrah al-Hāƙƙọh; 69:40.
ذِي قُوَّةٍ عِندَ ذِي ٱلۡعَرۡشِ مَكِينٖ
alágbára, ẹni pàtàkì ní ọ̀dọ̀ Ẹni t’Ó ni Ìtẹ́-ọlá,
مُّطَاعٖ ثَمَّ أَمِينٖ
ẹni tí wọ́n ń tẹ̀lé àṣẹ rẹ̀ níbẹ̀ yẹn (nínú sánmọ̀), olùfọkàntán.
وَمَا صَاحِبُكُم بِمَجۡنُونٖ
Àti pé ẹni yín (Ànábì Muhammad - kí ìkẹ́ àti ọlà Allāhu máa bá a -) kì í ṣe wèrè.
وَلَقَدۡ رَءَاهُ بِٱلۡأُفُقِ ٱلۡمُبِينِ
Ó kúkú rí i nínú òfurufú kedere.[1]
[1] Ìyẹn ni pé, Ànábì Muhammad - kí ìkẹ́ àti ọlà Allāhu máa bá a - fojú ara rẹ̀ rí Mọlāika Jibrīl - kí ọlà Allāhu máa bá a - nínú òfurufú kedere.
وَمَا هُوَ عَلَى ٱلۡغَيۡبِ بِضَنِينٖ
Àti pé kì í ṣe ahun (tàbí ẹni-afurasí) lórí ìró ìkọ̀kọ̀ (tí A fi ránṣẹ́ sí i).
وَمَا هُوَ بِقَوۡلِ شَيۡطَٰنٖ رَّجِيمٖ
Al-Ƙur’ān kì í sì ṣe ọ̀rọ̀ (tí A fi rán) aṣ-Ṣaetọ̄n, ẹni ẹ̀kọ̀.
فَأَيۡنَ تَذۡهَبُونَ
Nítorí náà, ibo l’ẹ̀ ń lọ?
إِنۡ هُوَ إِلَّا ذِكۡرٞ لِّلۡعَٰلَمِينَ
Kí sì ni al-Ƙur’ān bí kò ṣe ìrántí fún gbogbo ẹ̀dá.
لِمَن شَآءَ مِنكُمۡ أَن يَسۡتَقِيمَ
(Ó wà) fún ẹni tí ó bá fẹ́ nínú yín láti dúró déédé.
وَمَا تَشَآءُونَ إِلَّآ أَن يَشَآءَ ٱللَّهُ رَبُّ ٱلۡعَٰلَمِينَ
Ẹ̀yin kò sì níí fẹ́ (láti dúró déédé) àyàfi tí Allāhu bá fẹ́, Olúwa gbogbo ẹ̀dá.
At-Takwir
Play