إِذَا وَقَعَتِ ٱلۡوَاقِعَةُ
Nígbà tí Ìṣẹ̀lẹ̀ (Àjíǹde) bá ṣẹlẹ̀,
الواقعة
Read Surah Al-Waqiah in Yoruba (الواقعة) with Arabic text, Yoruba translation, and audio recitation. Chapter 56 of the Holy Quran, 96 verses — free online.
Quran in Yoruba · all 114 Surahs
إِذَا وَقَعَتِ ٱلۡوَاقِعَةُ
Nígbà tí Ìṣẹ̀lẹ̀ (Àjíǹde) bá ṣẹlẹ̀,
لَيۡسَ لِوَقۡعَتِهَا كَاذِبَةٌ
- kò sí irọ́ kan nípa ìṣẹ̀lẹ̀ rẹ̀-
خَافِضَةٞ رَّافِعَةٌ
ó máa mú (àwọn kan) wálẹ̀ (sínú Iná), ó sì máa gbé (àwọn kan) sókè (nínú Ọgbà Ìdẹ̀ra).
إِذَا رُجَّتِ ٱلۡأَرۡضُ رَجّٗا
Nígbà tí wọ́n bá mi ilẹ̀ tìtì ní mímìtìtì,
وَبُسَّتِ ٱلۡجِبَالُ بَسّٗا
àti nígbà tí Wọ́n bá fọ́ àwọn àpáta ní fífọ́ wómúwómú,
فَكَانَتۡ هَبَآءٗ مُّنۢبَثّٗا
- wọ́n sì máa di eruku àfẹ́dànù -
وَكُنتُمۡ أَزۡوَٰجٗا ثَلَٰثَةٗ
ẹ̀yin sì máa jẹ́ oríṣi mẹ́ta.[1]
[1] Ọgbà Ìdẹ̀ra wà fún ìjọ ọ̀tún, Ọgbà Iná sì wá fún ìjọ òsì. Àmọ́, Allāhu - tó ga jùlọ - ṣe àtúnpín ìjọ ọ̀tún sí ìjọ ọ̀tún àti ìjọ aṣíwájú nítorí pé, ìgbádùn ìkíní kejì yàtọ̀ gan-an síra wọn.
فَأَصۡحَٰبُ ٱلۡمَيۡمَنَةِ مَآ أَصۡحَٰبُ ٱلۡمَيۡمَنَةِ
Àwọn èrò ọwọ́ ọ̀tún, kí ni (ó máa ti dára tó fún) àwọn èrò ọwọ́ ọ̀tún?
وَأَصۡحَٰبُ ٱلۡمَشۡـَٔمَةِ مَآ أَصۡحَٰبُ ٱلۡمَشۡـَٔمَةِ
Àwọn èrò ọwọ́ òsì, kí ni (ó máa ti burú tó fún) àwọn èrò ọwọ́ òsì?
وَٱلسَّٰبِقُونَ ٱلسَّٰبِقُونَ
Àwọn aṣíwájú sì ni àwọn aṣíwájú.
أُوْلَٰٓئِكَ ٱلۡمُقَرَّبُونَ
Àwọn wọ̀nyẹn ni alásùn-únmọ́ (Allāhu)
فِي جَنَّٰتِ ٱلنَّعِيمِ
nínú Ọgbà Ìdẹ̀ra.
ثُلَّةٞ مِّنَ ٱلۡأَوَّلِينَ
Wọ́n pọ̀ nínú àwọn ẹni àkọ́kọ́.
وَقَلِيلٞ مِّنَ ٱلۡأٓخِرِينَ
Wọ́n sì kéré nínú àwọn ẹni Ìkẹ́yìn.
عَلَىٰ سُرُرٖ مَّوۡضُونَةٖ
(Wọn yóò wà) lórí ìtẹ́ tí wọ́n fi góòlù hun.
مُّتَّكِـِٔينَ عَلَيۡهَا مُتَقَٰبِلِينَ
Wọn yóò rọ̀gbọ̀kú sórí rẹ̀, wọn sì máa dojú kọra wọn.
يَطُوفُ عَلَيۡهِمۡ وِلۡدَٰنٞ مُّخَلَّدُونَ
Àwọn ọ̀dọ́kùnrin tí kò níí darúgbó yó sì máa lọ bọ̀ láààrin wọn
بِأَكۡوَابٖ وَأَبَارِيقَ وَكَأۡسٖ مِّن مَّعِينٖ
pẹ̀lú àwọn ife omi, ohun ìrọmi fẹ̀ǹfẹ̀ àti ife ọtí aládùn láti inú odò kan tó ń ṣàn (káà kiri ọ̀dọ̀ wọn).
لَّا يُصَدَّعُونَ عَنۡهَا وَلَا يُنزِفُونَ
Kò níí fọ́ wọn lórí; kò sì níí mú wọn húnrìrà.
وَفَٰكِهَةٖ مِّمَّا يَتَخَيَّرُونَ
Èso tí wọn yóò máa ṣẹ̀ṣà nínú rẹ̀ (tún wà fún wọn).
وَلَحۡمِ طَيۡرٖ مِّمَّا يَشۡتَهُونَ
Àti ẹran ẹyẹ, èyí tí wọ́n ń fẹ́ (yó wà fún wọn).
وَحُورٌ عِينٞ
Àwọn obìnrin ẹlẹ́yinjú ẹgẹ́ (tún wà fún wọn).
كَأَمۡثَٰلِ ٱللُّؤۡلُوِٕ ٱلۡمَكۡنُونِ
Wọ́n dà bí àlúùúlù (òkúta olówó-iye-bíye) tí wọ́n fi pamọ́ sínú apó rẹ̀.
جَزَآءَۢ بِمَا كَانُواْ يَعۡمَلُونَ
(Ìwọ̀nyí ni) ẹ̀san fún ohun tí wọ́n ń ṣe níṣẹ́.
لَا يَسۡمَعُونَ فِيهَا لَغۡوٗا وَلَا تَأۡثِيمًا
Wọn kò níí gbọ́ ìsọkúsọ àti ọ̀rọ̀ ẹ̀ṣẹ̀ nínú Ọgbà Ìdẹ̀ra.
إِلَّا قِيلٗا سَلَٰمٗا سَلَٰمٗا
Àyàfi ọ̀rọ̀ àlàáfíà, àlàáfíà.
وَأَصۡحَٰبُ ٱلۡيَمِينِ مَآ أَصۡحَٰبُ ٱلۡيَمِينِ
Àwọn èrò ọwọ́ ọtún, kí ni (ó máa ti dára tó fún) àwọn èrò ọwọ́ ọtún?
فِي سِدۡرٖ مَّخۡضُودٖ
(Wọn yóò wà) ní ìdí igi tí kò ní ẹ̀gún,
وَطَلۡحٖ مَّنضُودٖ
àti ọ̀gẹ̀dẹ̀ tó so jìgbìnnì,
وَظِلّٖ مَّمۡدُودٖ
àti ibòji tó gbòòrò,
وَمَآءٖ مَّسۡكُوبٖ
àti omi tó ń ṣàn láì dáwọ́ dúró,
وَفَٰكِهَةٖ كَثِيرَةٖ
àti ọ̀pọ̀lọ́pọ̀ èso,
لَّا مَقۡطُوعَةٖ وَلَا مَمۡنُوعَةٖ
tí kò níí já (ní ọ̀dọ̀ wọn), kò sì níí dèèwọ̀ (fún wọn).
وَفُرُشٖ مَّرۡفُوعَةٍ
(Wọ́n máa wà lórí) ìtẹ́ tí wọ́n gbé sókè.
إِنَّآ أَنشَأۡنَٰهُنَّ إِنشَآءٗ
Dájúdájú Àwa dá (àwọn obìnrin Ọgbà Ìdẹ̀ra) ní ẹ̀dá kan (tó yàtọ̀ sí tayé).
فَجَعَلۡنَٰهُنَّ أَبۡكَارًا
A sì ṣe wọ́n ní wúńdíá,
عُرُبًا أَتۡرَابٗا
olólùfẹ́ ọkọ. Wọ́n sì dọ́gba ní ọjọ́ orí.
لِّأَصۡحَٰبِ ٱلۡيَمِينِ
(Wọ́n wà) fún àwọn èrò ọwọ́ ọ̀tún.
ثُلَّةٞ مِّنَ ٱلۡأَوَّلِينَ
Wọ́n pọ̀ nínú àwọn ẹni àkọ́kọ́.
وَثُلَّةٞ مِّنَ ٱلۡأٓخِرِينَ
Wọ́n tún pọ̀ nínú àwọn ẹni Ìkẹ́yìn.[1]
[1] Àwọn ẹni àkọ́kọ́ dúró fún àwọn ènìyàn láti àsìkò Ànábì Ādam títí di àsìkò Ànábì ‘Īsā - kí ọlà Allāhu máa bá wọn -. Àwọn ẹni Ìkẹ́yìn sì dúró fún ìjọ Ànábì wa nìkan - kí ìkẹ́ àti ọlà Allāhu máa bá a -.
وَأَصۡحَٰبُ ٱلشِّمَالِ مَآ أَصۡحَٰبُ ٱلشِّمَالِ
Àwọn èrò ọwọ́ òsì, kí ni (ó máa ti burú tó fún) àwọn èrò ọwọ́ òsì?
فِي سَمُومٖ وَحَمِيمٖ
(Wọn yóò wà) nínú atẹ́gùn gbígbóná (iná) àti omi tó gbóná parí,
وَظِلّٖ مِّن يَحۡمُومٖ
àti ní abẹ́ ibòji eléèéfín dúdú,
لَّا بَارِدٖ وَلَا كَرِيمٍ
kò tutù, kò sì dára.
إِنَّهُمۡ كَانُواْ قَبۡلَ ذَٰلِكَ مُتۡرَفِينَ
Dájúdájú wọ́n ti jẹ́ onígbẹdẹmukẹ ṣíwájú ìyẹn.
وَكَانُواْ يُصِرُّونَ عَلَى ٱلۡحِنثِ ٱلۡعَظِيمِ
Wọ́n sì máa ń ṣoríkunkun lórí ẹ̀ṣẹ̀ ńlá.
وَكَانُواْ يَقُولُونَ أَئِذَا مِتۡنَا وَكُنَّا تُرَابٗا وَعِظَٰمًا أَءِنَّا لَمَبۡعُوثُونَ
Wọ́n sì máa ń wí pé: “Ṣé nígbà tí a bá di òkú, tí a sì di erùpẹ̀ àti egungun, ǹjẹ́ Wọn yóò tún gbé wa dìde ni?
أَوَءَابَآؤُنَا ٱلۡأَوَّلُونَ
Ṣé àti àwọn bàbá wa, àwọn ẹni àkọ́kọ́?”
قُلۡ إِنَّ ٱلۡأَوَّلِينَ وَٱلۡأٓخِرِينَ
Sọ pé: “Dájúdájú àwọn ẹni àkọ́kọ́ àti àwọn ẹni Ìkẹ́yìn,
لَمَجۡمُوعُونَ إِلَىٰ مِيقَٰتِ يَوۡمٖ مَّعۡلُومٖ
dájúdájú A óò kó wọn jọ papọ̀ ní àkókò ọjọ́ kan tí A ti mọ̀.”
ثُمَّ إِنَّكُمۡ أَيُّهَا ٱلضَّآلُّونَ ٱلۡمُكَذِّبُونَ
Lẹ́yìn náà, dájúdájú ẹ̀yin olùṣìnà, olùpe-òdodo-nírọ́,
لَأٓكِلُونَ مِن شَجَرٖ مِّن زَقُّومٖ
dájúdájú ẹ̀yin máa jẹ nínú igi zaƙƙūm (igi iwọ).
فَمَالِـُٔونَ مِنۡهَا ٱلۡبُطُونَ
Ikùn yín sì máa kún bámúbámú fún (jíjẹ) igi náà.
فَشَٰرِبُونَ عَلَيۡهِ مِنَ ٱلۡحَمِيمِ
Ẹ̀yin yó sì máa mu omi tó gbóná parí lé e lórí.
فَشَٰرِبُونَ شُرۡبَ ٱلۡهِيمِ
Ẹ̀yin yóò máa mu ún ní ìmumi ràkúnmí tí òǹgbẹ ń gbẹ.
هَٰذَا نُزُلُهُمۡ يَوۡمَ ٱلدِّينِ
Èyí ni n̄ǹkan àlejò wọn ní Ọjọ́ ẹ̀san.
نَحۡنُ خَلَقۡنَٰكُمۡ فَلَوۡلَا تُصَدِّقُونَ
Àwa l’A ṣẹ̀dá yín. Kí ni kò jẹ́ kí ẹ gbàgbọ́ ní òdodo!
أَفَرَءَيۡتُم مَّا تُمۡنُونَ
Ẹ sọ fún Mi nípa àtọ̀ tí ẹ̀ ń dà jáde (sínú àpòlùkẹ́),
ءَأَنتُمۡ تَخۡلُقُونَهُۥٓ أَمۡ نَحۡنُ ٱلۡخَٰلِقُونَ
ṣé ẹ̀yin lẹ ṣẹ̀dá rẹ̀ ni tàbí Àwa l’A ṣẹ̀dá rẹ̀?
نَحۡنُ قَدَّرۡنَا بَيۡنَكُمُ ٱلۡمَوۡتَ وَمَا نَحۡنُ بِمَسۡبُوقِينَ
Àwa l’A yan kádàrá (ọjọ́) ikú fún gbogbo yín. Kò sì sí ẹni tó lè dá Wa lágara
عَلَىٰٓ أَن نُّبَدِّلَ أَمۡثَٰلَكُمۡ وَنُنشِئَكُمۡ فِي مَا لَا تَعۡلَمُونَ
láti yí irú yín padà (láti inú erùpẹ̀ sí alààyè), kí á sì ṣẹ̀dá yín (ní ọ̀tun) sínú ohun tí ẹ kò mọ̀ (nínú àwọn ìrísí).
وَلَقَدۡ عَلِمۡتُمُ ٱلنَّشۡأَةَ ٱلۡأُولَىٰ فَلَوۡلَا تَذَكَّرُونَ
Ẹ kúkú mọ ìṣẹ̀dá àkọ́kọ́ (pé láti ibi àìsí ni ẹ ti di alààyè), ẹ kò ṣe lo ìrántí?
أَفَرَءَيۡتُم مَّا تَحۡرُثُونَ
Ẹ sọ fún Mi nípa n̄ǹkan tí ẹ̀ ń gbìn sínú ilẹ̀,
ءَأَنتُمۡ تَزۡرَعُونَهُۥٓ أَمۡ نَحۡنُ ٱلزَّٰرِعُونَ
ṣé ẹ̀yin l’ẹ̀ ń jẹ́ kí ó hù jáde tàbí Àwa l’À ń jẹ́ kí ó hù jáde?
لَوۡ نَشَآءُ لَجَعَلۡنَٰهُ حُطَٰمٗا فَظَلۡتُمۡ تَفَكَّهُونَ
Tí A bá fẹ́ ni, Àwa ìbá sọ ọ́ di gbígbẹ, ẹ̀yin yó sì máa ṣèèmọ̀ (tí ẹ óò máa ká àbámọ̀).
إِنَّا لَمُغۡرَمُونَ
(Ẹ̀yin yó sì wí pé:) “Dájúdájú àwa ti di onígbèsè.”
بَلۡ نَحۡنُ مَحۡرُومُونَ
(Àwọn mìíràn yó sì wí pé:) “Rárá o! Wọ́n ṣe ìkórè oko ní èèwọ̀ fún wa ni.”
أَفَرَءَيۡتُمُ ٱلۡمَآءَ ٱلَّذِي تَشۡرَبُونَ
Ẹ sọ fún mi nípa omi tí ẹ̀ ń mu,
ءَأَنتُمۡ أَنزَلۡتُمُوهُ مِنَ ٱلۡمُزۡنِ أَمۡ نَحۡنُ ٱلۡمُنزِلُونَ
ṣé ẹ̀yin l’ẹ̀ ń sọ̀ ọ́ kalẹ̀ láti inú ẹ̀ṣújò ni tàbí Àwa l’À ń sọ̀ ọ́ kalẹ̀?
لَوۡ نَشَآءُ جَعَلۡنَٰهُ أُجَاجٗا فَلَوۡلَا تَشۡكُرُونَ
Tí A bá fẹ́ ni, Àwa ìbá ṣe é ní omi tó móró. Ẹ ò ṣe máa dúpẹ́?
أَفَرَءَيۡتُمُ ٱلنَّارَ ٱلَّتِي تُورُونَ
Ẹ sọ fún Mi nípa iná tí ẹ̀ ń dá,
ءَأَنتُمۡ أَنشَأۡتُمۡ شَجَرَتَهَآ أَمۡ نَحۡنُ ٱلۡمُنشِـُٔونَ
ṣé ẹ̀yin l’ẹ ṣẹ̀dá igi rẹ̀ ni tàbí Àwa ni Aṣẹ̀dá?
نَحۡنُ جَعَلۡنَٰهَا تَذۡكِرَةٗ وَمَتَٰعٗا لِّلۡمُقۡوِينَ
Àwa ṣe iná ayé ní ìrántí (fún Iná ọ̀run) àti n̄ǹkan èlò fún àwọn onírìn-àjò.
فَسَبِّحۡ بِٱسۡمِ رَبِّكَ ٱلۡعَظِيمِ
Nítorí náà, ṣàfọ̀mọ́ fún orúkọ Olúwa rẹ, Atóbi.
۞ فَلَآ أُقۡسِمُ بِمَوَٰقِعِ ٱلنُّجُومِ
Nítorí náà, Mò ń fi àwọn àyè tí ìkọ̀ọ̀kan gbólóhùn al-Ƙur’ān wà nínú sánmọ̀ búra.[1]
[1] “Mọwāƙi‘u-nnujūm” tún lè túmọ̀ sí “àwọn ibùsọ̀ ìràwọ̀ nínú sánmọ̀”. Nítorí náà, ìtúmọ̀ mìíràn fún āyah yìí nìyí: “Nítorí náà, Mò ń fi àwọn ibùsọ̀ ìràwọ̀ búra.”
وَإِنَّهُۥ لَقَسَمٞ لَّوۡ تَعۡلَمُونَ عَظِيمٌ
Dájúdájú ìbúra ńlá ni, tí ẹ bá mọ̀.
إِنَّهُۥ لَقُرۡءَانٞ كَرِيمٞ
Dájúdájú (al-Ƙur’ān) ni n̄ǹkan kíké alápọ̀n-ọ́nlé.
فِي كِتَٰبٖ مَّكۡنُونٖ
Ó wà nínú Tírà kan tí wọ́n ń fi ààbò bò (ìyẹn Laohul-Mahfūṭḥ).
لَّا يَمَسُّهُۥٓ إِلَّا ٱلۡمُطَهَّرُونَ
Kò sí ẹni tó lè fọwọ́ kàn án (ní ọ̀dọ̀ Allāhu) àfi àwọn ẹni mímọ́ (ìyẹn, àwọn mọlāika).
تَنزِيلٞ مِّن رَّبِّ ٱلۡعَٰلَمِينَ
Wọ́n sọ al-Ƙur’ān kalẹ̀ láti ọ̀dọ̀ Olúwa gbogbo ẹ̀dá.
أَفَبِهَٰذَا ٱلۡحَدِيثِ أَنتُم مُّدۡهِنُونَ
Nítorí náà, ṣé ọ̀rọ̀ (al-Ƙur’ān) yìí l’ẹ̀ ń pè ní irọ́?
وَتَجۡعَلُونَ رِزۡقَكُمۡ أَنَّكُمۡ تُكَذِّبُونَ
Ẹ sì ń sọ ìdúpẹ́ arísìkí yín di pé dájúdájú ẹ̀ ń pe òdodo ní irọ́.[1]
[1] Ìyẹn ni pé, àwọn ọ̀ṣẹbọ ń dúpẹ́ fún ìràwọ̀ nítorí pé, wọ́n gbàgbọ́ pé òhun l’ó ń rọ̀jò lẹ́yìn Allāhu. Irọ́ àti àìgbàgbọ́ nínú Allāhu ni èyí. Allāhu - tó ga jùlọ - ni Ẹni t’Ó ń rọ̀jò fún ẹ̀dá Rẹ̀.
فَلَوۡلَآ إِذَا بَلَغَتِ ٱلۡحُلۡقُومَ
Kí ni ó máa ti rí (fún yín) nígbà tí ẹ̀mí (yín) bá dé ọ̀nà ọ̀fun,
وَأَنتُمۡ حِينَئِذٖ تَنظُرُونَ
tí ẹ̀yin yó sì máa wò bọ̀ọ̀ nígbà yẹn?
وَنَحۡنُ أَقۡرَبُ إِلَيۡهِ مِنكُمۡ وَلَٰكِن لَّا تُبۡصِرُونَ
Àwa sì súnmọ́ ọn ju ẹ̀yin lọ, ṣùgbọ́n ẹ̀yin kò ríran.[1]
[1] Ẹ wo ìtọsẹ̀-ọ̀rọ̀ sūrah al-Mujādilah; 58:7.
فَلَوۡلَآ إِن كُنتُمۡ غَيۡرَ مَدِينِينَ
Ẹ̀yin kò ṣe jẹ́ ẹni tí A ò níí gbẹ̀san lára rẹ̀,
تَرۡجِعُونَهَآ إِن كُنتُمۡ صَٰدِقِينَ
kí ẹ sì dá (ẹ̀mí tí ó fẹ́ bọ́) padà, tí ẹ bá jẹ́ olódodo.
فَأَمَّآ إِن كَانَ مِنَ ٱلۡمُقَرَّبِينَ
Ní ti ẹni tí ó bá wà nínú àwọn alásùn-únmọ́ (Wa),
فَرَوۡحٞ وَرَيۡحَانٞ وَجَنَّتُ نَعِيمٖ
ìsinmi, èsè tó dára àti Ọgbà Ìdẹ̀ra (ni tirẹ̀).
وَأَمَّآ إِن كَانَ مِنۡ أَصۡحَٰبِ ٱلۡيَمِينِ
Ní ti ẹni tí ó bá wà nínú àwọn èrò ọwọ́ ọ̀tún,
فَسَلَٰمٞ لَّكَ مِنۡ أَصۡحَٰبِ ٱلۡيَمِينِ
àlàáfíà ni fún ọ láààrin àwọn èrò ọwọ́ ọ̀tún.
وَأَمَّآ إِن كَانَ مِنَ ٱلۡمُكَذِّبِينَ ٱلضَّآلِّينَ
Ní ti ẹni tí ó bá wà nínú àwọn olùpe-òdodo-nírọ́, àwọn olùṣìnà,
فَنُزُلٞ مِّنۡ حَمِيمٖ
n̄ǹkan àlejò (wọn) ni omi tó gbóná parí
وَتَصۡلِيَةُ جَحِيمٍ
àti wíwọ inú iná Jẹhīm.
إِنَّ هَٰذَا لَهُوَ حَقُّ ٱلۡيَقِينِ
Dájúdájú èyí, òhun ni òdodo tó dájú.
فَسَبِّحۡ بِٱسۡمِ رَبِّكَ ٱلۡعَظِيمِ
Nítorí náà, ṣàfọ̀mọ́ fún orúkọ Olúwa rẹ, Atóbi.
Al-Waqiah
Play